Gbọ Audio Ìròyìn Òmìnira

Ó pẹ́ tí a ti máa ń sọ pé àwọn ọmọ Íbò gọ̀, wọ́n nf’ẹnu họ’ra. Ṣé láìpẹ́ yí ni ìkan nínú wọn tún bọ́ sórí ẹ̀rọ ayélujára  tó sì ń wí pé, àwọn Yorùbá ń bẹ̀rù láti kúrò nínú Nàìjíríà.

Ẹ jọ̀wọ́ ẹ bá wa béèrè lọ́wọ́ alákọrí rẹ̀ bóyá ihò-ilẹ̀ ló ń gbé, tí kò fi mọ̀ pé Yorùbá ti kúrò lára Nàìjíríà ó tí di ọdún kan àti oṣù mẹ́san báyìí.

Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn agbésùnmọ̀mí Nàìjíríà ṣì ń ṣorí kunkun, ṣùgbọ́n tí a mọ̀ pé Olódùmarè máa ṣí wọn ní’díì kúrò lórí ilẹ̀ wa láìpẹ́.

Ṣùgbọ́n àrùn kan tí ó nṣe àwọn af’ẹnuhọ’ra Íbò wọ̀nyí ni pé, ẹni tí kò bá tíì máa làágùn, kí ó máa ṣe hílà-hílo káàkiri ìgboro, ọpọlọ wọn ò gbà pé irú ẹni bẹ́ẹ̀ nṣiṣẹ́.

Ọpọlọ ni Yorùbá fi ń jà; ṣùgbọ́n àwọn  Íbò kò gbà pé ìjà ọpọlọ ni ọ̀rọ̀ tó wà nílẹ̀ yí, eré kí àwọn ṣáà máa fẹ̀’fun kiri títì ni wọ́n gbà pé ó jẹ́ ìjàǹgbara.

The Democratic Republic of the Yoruba also known in the Yoruba history as Yoruba Nation, Yoruba Kingdom, Yoruba Land and Yoruba Country is the newest nation in the world. The 55th nation in Africa and 17th in Western Africa as of 12th April 2024. Yoruba is know a sovereign nation and its no longer part of Nigeria.
Ìròyìn Òmìnira Olojoojumọ – Bèrè fún ẹ̀da títí rẹ!

Ojú wọn ló máa ṣe, nígbàti ìjọba Democratic Republic of the Yoruba (D.R.Y) bá wọlé sí àwọn oríkò ilé-iṣẹ́-ìjọba wa gbogbo; àá wá wo ibi tí gbogbo àwọn òmùgọ̀ yí máa fojú sí nígbà náà.

Gẹ́gẹ́ bí akọ̀ròyìn wa kan ti ṣe àfihàn ọ̀rọ̀ tí ọmọ Íbò yí nsọ; ó pèé ní ‘Gàlègàlè àwọn ẹlẹ́nu mímú j’abẹlọ ọmọ Íbò.’ Ọ̀rọ̀ gidi tó ṣe àpèjúwe òmùgọ̀ ọmọ Íbò ọ̀hún nì yẹn.

Ó tún sọ ọ̀rọ̀ rẹ̀ dé bi wí pé, òun ò ní fara mọ́ kí ọmọ Yorùbá ó ṣe olórí Nàìjíríà mọ́. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé kò sí èyí tó kàn wá nípa ìyẹn, ó fi hàn gedegbe pé àwọn òpònú Íbò wọ̀nyí kò mọ ń kan tí wọ́n fẹ́ gan-an gan.

Apá kan ẹnu wọn á máa sọ̀rọ̀ ipò wọn ní ìlú Nàìjíríà, apá kejì á máa sọ̀rọ̀ pínpínyà kúrò ní Nàìjíríà, nígbà tí wọ́n kò mọ èyí tó kàn.

A dúpẹ́ pé Orílẹ̀-Èdè Olómìnira Tiwantiwa ti Yorùbá (D.R.Y) ti jẹ́ orílẹ̀-èdè aṣèjọba-ara-ẹni láti ọjọ́ kéjìlá oṣù Igbe ẹgbàá ọdún ó lé mẹ́rinlélógún.

Pẹ̀lú àṣẹ Èdùmàrè, ní àìpẹ́ yí ni a máa rẹ́yìn Nàìjíríà tí wọ́n sì máa sá kúrò lórí ilẹ̀ wa.